9. Jábésì sì ní olá ju àwọn ẹ̀gbọ́n Rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá Rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jábésì wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
10. Jábésì sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí pé, “Áà, Ìwọ yóò bùkún fún, ìwọ yóò sì mú agbégbé mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mí mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ Rẹ̀
11. Kélúbù arákùnrin ṣúà, sì jẹ́ baba Méhírì, ẹni tí ó jẹ́ baba Ésítónì.
12. Ésítónì sì jẹ́ baba Bétí-ráfà, Páséà àti Téhína ti baba ìlú Náhásì. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Rékà.
13. Àwọn ọmọ Kénásì:Otíníẹ́lì àti Ṣéráíà.Àwọn ọmọ Ótiníẹ́lì:Hátatì àti Méónótaì.
14. Méónótaì sì ni baba Ófírà.Ṣéráíà sì jẹ́ baba Jóábù,baba Géhárásínù. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn onísọ́nà niwọ́n.
15. Àwọn ọmọ kálébù ọmọ Jéfúnè:Irú, Élà, àti Námù.Àwọn ọmọ Élà:Kénásì.
16. Àwọn ọmọ Jéhálélélì:Ṣífù, ṣífà, Tíríà àti Ásárélì.