Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 4:37-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Àti Ṣísà ọmọ ṣífì ọmọ Álónì, ọmọ Jédáíyà, ọmọ Ṣímírì ọmọ Ṣémáíyà.

38. Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ síi gidigidi,

39. Wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gédórì. Lọ títí dé ìlà òrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn

40. Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ará Ámù ni ó ń gbé bẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.

41. Ọkùnrin tí a kọ orúkọ Rẹ̀ sókè wà ní ọjọ́ Hésékíà ọba Júdà àti àwọn ibùgbé wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Máhúnì ẹni tí ó wà níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátapáta. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe jẹ́ ẹ̀rí títí di òníyìí. Nígbà náà wọ́n sì ń gbé ní iye wọn, nítorí pé koríko wà fún àwọn agbo ẹran wọn.

42. Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Síméónì, sin pẹ̀lú Pélátíà, Néáríà, Réfáíà àti Úsíélì, àwọn ọmọ Íṣì, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Ṣéírì.

43. Wọ́n sì pa àwọn ará Ámálékì tí ó kù àwọn tí ó ti sá lọ, wọ́n sì ti ń gbé bẹ̀ láti òní yìí.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 4