Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 4:3-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Étanílù:Jésírélì, Ísímà, Ídíbásì, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Sélélípónì

4. Pénúélì sì ni baba Gédórì, àti Édérì baba Húṣà.Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Húrì, Àkọ́bí Éfúrátà àti baba Bẹ́tílẹ́hẹ́mù.

5. Áṣárì bàbá Jékóà sì ní aya méjì, Hélà àti Nárà.

6. Nárà sì bí Áhúsámù, Héférì Téménì àti Háhásítarì. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Nátà.

7. Àwọn ọmọ Hélà:Ṣérétì Ṣóárì, Étanì,

8. Àti kósì ẹnítí ó jẹ́ baba Ánúbì àti Hásóbébà àti ti àwọn Ẹ̀yà Áháríhélì ọmọ Hárúmù.

9. Jábésì sì ní olá ju àwọn ẹ̀gbọ́n Rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá Rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jábésì wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”

10. Jábésì sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí pé, “Áà, Ìwọ yóò bùkún fún, ìwọ yóò sì mú agbégbé mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mí mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ Rẹ̀

11. Kélúbù arákùnrin ṣúà, sì jẹ́ baba Méhírì, ẹni tí ó jẹ́ baba Ésítónì.

12. Ésítónì sì jẹ́ baba Bétí-ráfà, Páséà àti Téhína ti baba ìlú Náhásì. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Rékà.

13. Àwọn ọmọ Kénásì:Otíníẹ́lì àti Ṣéráíà.Àwọn ọmọ Ótiníẹ́lì:Hátatì àti Méónótaì.

14. Méónótaì sì ni baba Ófírà.Ṣéráíà sì jẹ́ baba Jóábù,baba Géhárásínù. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn onísọ́nà niwọ́n.

15. Àwọn ọmọ kálébù ọmọ Jéfúnè:Irú, Élà, àti Námù.Àwọn ọmọ Élà:Kénásì.

16. Àwọn ọmọ Jéhálélélì:Ṣífù, ṣífà, Tíríà àti Ásárélì.

17. Àwọn ọmọ Ésírà:Jétẹ́rì, Mérédì, Éférì àti Jálónì. Ọ̀kan lára àwọn aya Mérédì sì bí Míríámù, ṣámáì àti Íṣíbà baba Éṣítémóà.

18. Aya Rẹ̀ Jéhúdijà sì bí Jérédì baba Gédórì, Hébérì baba sókè àti Jékútíẹ́lì bàbá Sánóà. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọbìnrin ọmọ Bítíà ẹni ti Mérédì ti fẹ́.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 4