Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 24:4-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. A rí ọ̀pọ̀ àwọn olórí lára àwọn ọmọ Élíásérì ju lára àwọn ọmọ Ítamárì lọ, wọ́n sì pín wọn lẹ́sẹ lẹ́sẹ: mẹ́rindínlógún (16) olórí láti ìdílé ọmọ Élíásérì ìran wọn àti olórí méjọ ìdílé láti ara àwọn ọmọ Ítamárì.

5. Wọ́n sì pín wọn lótìítọ́ nípa yíya ìpín, nítorí àwọn olórí ibi mímọ́ àti àwọn olorí ilé Ọlọ́run wà láàrin àwọn ọmọ méjèèjì Élíásérì àti Ìtamárì.

6. Ṣémáíà ọmọ Nétanélì, akọ̀wé ọ̀kan lára àwọn ọmọ Léfì sì kọ orúkọ wọn níwájú ọba àti àwọn ìjòyè: Ṣádókù Àlùfáà, Áhímélékì ọmọ Ábíátarì àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà tí a mú láti ọ̀dọ̀ Éléásári àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ Ítamárì.

7. Ìpín èkíní jáde sí Jéhóíáríbù,èkejì sí Jédáià,

8. Ẹlẹ́kẹta sì ni Hárímù,ẹ̀kẹ́rin sì ní Ṣéórímù,

9. Ẹ̀karùn-ún sì ni Maíkíyà,ẹlẹkẹ́fà sì ni Míjámínì,

10. Ẹ̀kẹ́je sì ni Hakósì,ẹlẹ́kẹ́jọ sí ni Ábíjà,

11. Ẹkẹ́sàn sì ni Jésúà,ẹ̀kẹ́wà sì ni Ṣékáníà,

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 24