Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 16:34-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Fi ọpẹ fún Olúwa, nítórí tí ó dára;ìfẹ́ ẹ Rẹ̀ dúró títí láé.

35. Sunkún jáde, “Gbà wá, Ọlọ́run Olùgbàlà a wa;kówajọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀ èdè,kí àwa kí ó lè fí ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn Rẹ̀.”

36. Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì,láé àti láéláé.Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé “Àmín” wọ́n sì Yin Olúwa.

37. Dáfídì fi Áṣáfù àti àwọn ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa láti jísẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.

38. Ó fí Óbédì-Edomù àti méjìdín láàdọ́rin (68) ẹlẹgbẹ́ ẹ Rẹ̀ làti siṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Óbédí-Édómú ọmọ Jédútúnì àti Hósà pẹ̀lú jẹ́ olútọ́jú ẹnu-ọ́nà.

39. Dáfídì fi Ṣádókù àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gíbíónì.

40. Láti gbé pẹpẹ ọrẹ sísun déédé, àárọ̀ àti Ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Ísírẹ́lì.

41. Pẹ̀lú wọn ni Hémánì àti Jédútúnì àti ìyókù tí a mú àti yàn nípaṣẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa Nítorí tí ìfẹ́ Rẹ̀ dúró títí láéláé

42. Hémánì àti Jédútúnì ni wọ́n dúró fún fifọn ìpè àti Ṣíḿibálì àti fún títa ohun èlò yòókù fún orin yíyàsọ́tọ̀. Àwọn ọmọ Jédútúnì wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.

43. Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé láti lọ bùkún ìdílé Rẹ̀

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 16