Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 16:30-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Wárìrì níwájú Rẹ̀, gbogbo ayé!Ayé sì fi ìdímúlẹ̀; a kò sì le è síi.

31. Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀ Jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn;Jẹ́ kí wọn kí ó sọ láàárin àwọn orílẹ̀ èdè, pé “Olúwa jọba!”

32. Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, ati gbogbo ohun tí ó wà nínú Rẹ̀;Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú Rẹ̀!

33. Nígbà náà ni igi ti ọ̀dàn yóò kọrin,Wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, Nítorí tí ó wá láti sèdájọ́ ayé.

34. Fi ọpẹ fún Olúwa, nítórí tí ó dára;ìfẹ́ ẹ Rẹ̀ dúró títí láé.

35. Sunkún jáde, “Gbà wá, Ọlọ́run Olùgbàlà a wa;kówajọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀ èdè,kí àwa kí ó lè fí ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn Rẹ̀.”

36. Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì,láé àti láéláé.Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé “Àmín” wọ́n sì Yin Olúwa.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 16