Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 16:22-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi;Má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”

23. Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé;ẹ máa fi ìgbàlà Rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.

24. Kéde ìgbàlà à Rẹ̀ láàárin àwọn orílẹ̀-èdè,ohun ìyàlẹ́nu tí ó se láàrin gbogbo ènìyàn.

25. Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ Jùlọ;òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwon Ọlọ́run lọ.

26. Nítorí gbogbo àwọn Ọlọ́run orílẹ̀ èdè jẹ́ àwọn òrìsà,ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.

27. Dídán àti ọlá-ńlá ni ó wà ní wájú Rẹ̀;agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé Rẹ̀.

28. Fifún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè,ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa,

29. fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ Rẹ̀.Gbé ọrẹ kí ẹ sì wá ṣíwájú Rẹ̀;Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ Rẹ̀.

30. Wárìrì níwájú Rẹ̀, gbogbo ayé!Ayé sì fi ìdímúlẹ̀; a kò sì le è síi.

31. Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀ Jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn;Jẹ́ kí wọn kí ó sọ láàárin àwọn orílẹ̀ èdè, pé “Olúwa jọba!”

32. Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, ati gbogbo ohun tí ó wà nínú Rẹ̀;Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú Rẹ̀!

33. Nígbà náà ni igi ti ọ̀dàn yóò kọrin,Wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, Nítorí tí ó wá láti sèdájọ́ ayé.

34. Fi ọpẹ fún Olúwa, nítórí tí ó dára;ìfẹ́ ẹ Rẹ̀ dúró títí láé.

35. Sunkún jáde, “Gbà wá, Ọlọ́run Olùgbàlà a wa;kówajọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀ èdè,kí àwa kí ó lè fí ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn Rẹ̀.”

36. Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì,láé àti láéláé.Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé “Àmín” wọ́n sì Yin Olúwa.

37. Dáfídì fi Áṣáfù àti àwọn ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa láti jísẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.

38. Ó fí Óbédì-Edomù àti méjìdín láàdọ́rin (68) ẹlẹgbẹ́ ẹ Rẹ̀ làti siṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Óbédí-Édómú ọmọ Jédútúnì àti Hósà pẹ̀lú jẹ́ olútọ́jú ẹnu-ọ́nà.

39. Dáfídì fi Ṣádókù àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gíbíónì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 16