Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 15:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ìgbà tí Dáfídì ti kọ́ ilé fún ara Rẹ̀ ní ìlú Dáfídì. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.

2. Nígbà náà Dáfídì wí pé, Kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Léfì ni ó lè gbé Àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpóti ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú Rẹ̀ títí láé.

3. Dáfídì kó gbogbo àwon ọmọ Ísírélì jọ ní Jérúsálẹ́mù láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèṣè sílẹ̀ fún un.

4. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Árónì àti àwọn ọmọ Léfì tí Dáfídì pèjọ papọ̀:

5. Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kóhátì;Úríélì olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

6. Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Mórárì;Ásaíà olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

7. Àádóje nínú àwọn ọmọ Gésóní;Jóẹ́lì olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

8. Igba nínú àwọn ọmọ Élísáfálì;Ṣémáíà olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

9. Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hébírónì;Élíélì olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

10. Méjìléláàdọ́fà nínú àwọn ọmọ Húsíélì;Ámínádábù olórí àti àwọn ẹbí Rẹ̀.

11. Dáfídì sì ránṣẹ́ pe Ṣádókù, Ábíátarì tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Úríélì, Ásáíà. Jóẹ́lì, Ṣémáíà, Élíélì àti Ámínádábù tí wọ́n jẹ́ Léfì.

12. Ó sì fí fún wọn pé, Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Léfì; ẹ̀yin àti àwọn Léfì ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí-ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 15