5. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, à ní ọ̀pọ̀ Ọlọ́run kékèké mìíràn ní ọ̀run àti ní ayé (gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ “Ọlọ́run” ṣe wa náà ní ọ̀pọ̀ “Olúwa” wa).
6. Ṣùgbọ́n fún àwa Ọlọ́run kan ní ó wa, Baba, lọ́wọ́ ẹni tí ó dá ohun gbogbo, àti ti ẹni tí gbogbo wa í ṣe, àti Olúwa kan soso Jésù Kírísítì, nípaṣẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo wà, àti àwa nípaṣẹ̀ rẹ̀.
7. Ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo ènìyàn lo mọ èyí: Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn tí ó ti ń bọ̀rìṣà lọ́jọ́ tó ti pẹ́ títí di ìsinsinyìí jẹ ẹ́ bí ohun tí a fi rúbọ sí òrìṣà; àti ẹ̀rì-ọkàn wọn tí ó ṣe àìlera sì di aláìmọ́.
8. Ṣùgbọ́n oúnjẹ kò mú wa súnmọ́ Ọlọ́run, nítorí pé kì í ṣe bí àwa bá jẹun ni àwa buru julọ tàbí nígbà tí a kò jẹ ni àwa dára jùlọ.