17. Èyí ni ohun tí Olúwa wíOlùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì:“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ,tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
18. Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tísílẹ̀ sí àṣẹ mi,àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò,àti òdodo rẹ bí ìgbì òkun.
19. Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí i yanrìn,àwọn ọmọ yín bí i horo ọkà tí a kò lè kà tán;orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúròtàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
20. Fi Bábílónì sílẹ̀,sá fún àwọn ará Bábílónì,ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀kí o sì kéde rẹ̀.Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé;wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jákọ́bù nídè.”
21. Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọnkọjá nínú ihà;ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta;ó fọ́ àpátaomi sì tú jáde.
22. “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí,“Fún àwọn ìkà.”