1. Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Ásà, Básà ọba Ísírẹ́lì gòkè wá sí Júdà ó sì kọlu Rámà, láti ma bàá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Ásà ọba Júdà lọ.
2. Nígbà náà ni Ásà mú wúrà àti fàdákà jáde ninú ilé ìsúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránsẹ́ sí Bẹni-Hádádì ọba Árámù, ẹni tí ń gbé ní Dámásíkù, ó wí pé,
3. “Májẹ̀mu kan wà láàrin èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrin baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránsẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mu tí o bá Básà ọba Ísirẹ́lì dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi”