Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Rut 4:12-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

12. Ki ile rẹ ki o si dabi ile Peresi, ẹniti Tamari bi fun Juda, nipa irú-ọmọ ti OLUWA yio fun ọ lati ọdọ ọmọbinrin yi.

13. Boasi si mú Rutu, on si di aya rẹ̀; nigbati o si wọle tọ̀ ọ, OLUWA si mu ki o lóyun, o si bi ọmọkunrin kan.

14. Awọn obinrin si wi fun Naomi pe, Olubukun li OLUWA, ti kò fi ọ silẹ li ainí ibatan li oni, ki o si jẹ́ olokikí ni Israeli.

15. On o si jẹ́ olumupada ẹmi rẹ, ati olutọju ogbó rẹ: nitori aya-ọmọ rẹ, ẹniti o fẹ́ ọ, ti o san fun ọ jù ọmọkunrin meje lọ, li o bi i.

16. Naomi si gbé ọmọ na, o si tẹ́ ẹ si owókan-àiya rẹ̀, o si di alagbatọ́ rẹ̀.

17. Awọn obinrin aladugbo rẹ̀ si sọ ọ li orukọ, wipe, A bi ọmọkunrin kan fun Naomi; nwọn si pè orukọ rẹ̀ ni Obedi: on ni baba Jesse, baba Dafidi.

18. Wọnyi ni iran Peresi: Peresi bi Hesroni;

19. Hesroni si bi Ramu, Ramu si bi Amminadabu;

20. Amminadabu si bi Naṣoni, Naṣoni si bi Salmoni;

21. Salmoni si bi Boasi, Boasi si bi Obedi;

22. Obedi si bi Jesse, Jesse si bi Dafidi.

Ka pipe ipin Rut 4