Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Neh 8:11-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

11. Bẹ̃ni awọn ọmọ Lefi mu gbogbo enia dakẹ jẹ, wipe, ẹ dakẹ, nitori mimọ́ ni ọjọ yi; ẹ má si ṣe banujẹ.

12. Gbogbo awọn enia lọ lati jẹ ati lati mu ati lati fi ipin ranṣẹ, ati lati yọ ayọ̀ nla, nitoriti ọ̀rọ ti a sọ fun wọn ye wọn.

13. Li ọjọ keji awọn olori awọn baba gbogbo awọn enia, awọn alufa, ati awọn ọmọ Lefi pejọ si ọdọ Esra akọwe, ki o le fi ọ̀rọ ofin ye wọn.

14. Nwọn si ri a kọ sinu iwe-ofin, ti Oluwa ti pa li aṣẹ nipa ọwọ Mose pe, ki awọn ọmọ Israeli gbe inu agọ ni àse oṣu keje:

15. Pe, ki nwọn funrere, ki nwọn kede ni gbogbo ilu wọn, ati ni Jerusalemu, wipe, Ẹ jade lọ si òke, ki ẹ si mu ẹka igi olifi, ẹka igi pine, ati ẹka igi matili (myrtle) imọ ọpẹ, ati ẹka igi ti o tobi, lati ṣe agọ gẹgẹ bi a ti kọ ọ.

16. Bẹ̃ni awọn enia na jade lọ, nwọn si mu wọn wá, nwọn pa agọ fun ara wọn, olukuluku lori orule ile rẹ̀, ati li àgbala wọn, ati li àgbala ile Ọlọrun, ati ni ita ẹnu-bode omi, ati ni ita ẹnu-bode Efraimu.

17. Gbogbo ijọ enia ninu awọn ti o pada bọ̀ lati oko-ẹrú si pa agọ, nwọn si gbe abẹ awọn agọ na: nitori lati akokò Joṣua ọmọ Nuni wá, titi di ọjọ na awọn ọmọ Israeli kò ṣe bẹ̃. Ayọ̀ nlanla si wà.

18. Esra si kà ninu iwe ofin Ọlọrun li ojojumọ, lati ọjọ kini titi de ọjọ ikẹhin. Nwọn si pa àse na mọ li ọjọ meje, ati lọjọ kẹjọ, nwọn ni apejọ ti o ni ìronu gẹgẹ bi iṣe wọn.

Ka pipe ipin Neh 8