Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jer 42:16-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

16. Yio si ṣe, idà ti ẹnyin bẹ̀ru, yio si le nyin ba ni ilẹ Egipti; ati ìyan, ti ẹnyin bẹ̀ru, yio tẹle nyin girigiri nibẹ ni Egipti; nibẹ li ẹnyin o si kú.

17. Bẹ̃ni gbogbo awọn ọkunrin ti nwọn gbe oju wọn si ati lọ si Egipti lati ṣatipo nibẹ; nwọn o kú, nipa idà, nipa ìyan, tabi nipa àjakalẹ-arun, ẹnikẹni ninu wọn kì yio kù, tabi kì o sala kuro ninu ibi ti emi o mu wá sori wọn.

18. Nitori bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun, Ọlọrun Israeli wi, pe, Gẹgẹ bi emi ti dà ibinu mi ati irunu mi sori awọn olugbe Jerusalemu; bẹ̃ni emi o dà irunu mi le nyin lori, ẹnyin ti yio lọ si Egipti: ẹnyin o si di ẹni-ègun, ati ẹni-iyanu, ati ẹ̀gan, ati ẹ̀sin; ẹnyin kì yio si tun ri ibi yi mọ.

19. Oluwa ti sọ niti nyin, ẹnyin iyokù Juda, ẹ má lọ si Egipti: ẹ mọ̀ dajudaju pe emi ti jẹri si nyin li oni yi.

20. Nitori ọkàn nyin li ẹnyin tanjẹ, nigbati ẹnyin rán mi si Oluwa, Ọlọrun nyin, wipe, Gbadura fun wa si Oluwa, Ọlọrun wa: ati gẹgẹ bi gbogbo eyi ti Oluwa Ọlọrun wa yio wi, bẹ̃ni ki o sọ fun wa, awa o si ṣe e.

21. Emi si ti sọ fun nyin loni; ṣugbọn ẹnyin kò gbọ́ ohùn Oluwa, Ọlọrun nyin, ati gbogbo eyi ti on ti ran mi si nyin.

22. Njẹ nitorina, ẹ mọ̀ dajudaju pe, ẹnyin o kú nipa idà, nipa ìyan, ati nipa àjakalẹ-arun, ni ibẹ na nibiti ẹnyin fẹ lati lọ iṣe atipo.

Ka pipe ipin Jer 42