Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jer 22:1-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. BAYI li Oluwa wi, Sọkalẹ lọ si ile ọba Juda, ki o si sọ ọ̀rọ yi nibẹ.

2. Si wipe, Gbọ́ ọ̀rọ Oluwa, ọba Juda, ti o joko ni itẹ Dafidi, iwọ, ati awọn iranṣẹ rẹ, ati awọn enia rẹ ti o wọle ẹnu-bode wọnyi.

3. Bayi li Oluwa wi; Mu idajọ ati ododo ṣẹ, ki o si gbà ẹniti a lọ lọwọ gbà kuro lọwọ aninilara, ki o máṣe fi agbara ati ìka lò alejo, alainibaba ati opó, bẹ̃ni ki o máṣe ta ẹ̀jẹ alaiṣẹ silẹ nihinyi.

4. Nitori bi ẹnyin ba ṣe nkan yi nitõtọ, nigbana ni awọn ọba yio wọle ẹnu-bode ilu yi, ti nwọn o joko lori itẹ Dafidi, ti yio gun kẹ̀kẹ ati ẹṣin, on, ati awọn iranṣẹ rẹ̀, ati enia rẹ̀.

5. Ṣugbọn bi ẹnyin kì yio ba gbọ́ ọ̀rọ wọnyi, Emi fi emitikarami bura, li Oluwa wi, pe, ile yi yio di ahoro.

6. Nitori bayi li Oluwa wi fun ile ọba Juda; Gileadi ni iwọ si mi, ori Lebanoni: sibẹ, lõtọ emi o sọ ọ di aginju, ati ilu ti a kò gbe inu wọn.

7. Emi o ya awọn apanirun sọtọ fun ọ, olukuluku pẹlu ihamọra rẹ̀: nwọn o si ke aṣayan igi kedari rẹ lulẹ, nwọn o si sọ wọn sinu iná.

8. Ọ̀pọlọpọ orilẹ-ède yio rekọja lẹba ilu yi, nwọn o wi, ẹnikan fun ẹnikeji rẹ̀ pe, Ẽṣe ti Oluwa ṣe bayi si ilu nla yi?

9. Nigbana ni nwọn o dahùn pe, nitoriti nwọn ti kọ̀ majẹmu Oluwa Ọlọrun wọn silẹ; ti nwọn fi ori balẹ fun ọlọrun miran, nwọn si sìn wọn.

10. Ẹ máṣe sọkun fun okú, bẹ̃ni ki ẹ máṣe pohùnrere rẹ̀, ṣugbọn ẹ sọkun ẹ̀dun fun ẹniti o nlọ, nitori kì yio pada wá mọ, kì yio si ri ilẹ rẹ̀ mọ.

11. Nitori bayi li Oluwa wi fun Ṣallumu, ọmọ Josiah, ọba Juda, ti o jọba ni ipo Josiah, baba rẹ̀, ti o jade kuro nihin pe, On kì yio pada wá mọ.

12. Ṣugbọn yio kú ni ibi ti a mu u ni igbèkun lọ, kì yio si ri ilẹ yi mọ.

Ka pipe ipin Jer 22