Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2. Kro 32:2-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. Nigbati Hesekiah ri pe Sennakeribu de, ti o fi oju si ati ba Jerusalemu jagun,

3. O ba awọn ijoye rẹ̀ ati awọn ọkunrin alagbara rẹ̀ gbìmọ, lati dí omi orisun wọnni, ti mbẹ lẹhin ilu: nwọn si ràn a lọwọ.

4. Bẹ̃li ọ̀pọlọpọ enia kojọ pọ̀, awọn ẹniti o dí gbogbo orisun, ati odò ti nṣàn la arin ilẹ na ja, wipe, Nitori kili awọn ọba Assiria yio ṣe wá, ki nwọn ki o si ri omi pupọ̀?

5. O mu ara rẹ̀ le pẹlu, o si mọ gbogbo odi ti o ti ya, o si gbé e ga de awọn ile-iṣọ, ati odi miran lode, o si tun Millo ṣe ni ilu Dafidi, o si ṣe ọ̀kọ ati apata li ọ̀pọlọpọ.

6. O si yàn awọn balogun lori awọn enia, o si kó wọn jọ pọ̀ sọdọ rẹ̀ ni ita ẹnu-bode ilu, o si sọ̀rọ iyanju fun wọn, wipe,

7. Ẹ mu ara le, ki ẹ si ṣe onigboya, ẹ má bẹ̀ru, bẹ̃ni ki aiya ki o máṣe fò nyin nitori ọba Assiria, tabi nitori gbogbo ọ̀pọlọpọ enia ti o wà pẹlu rẹ̀; nitori awọn ti o pẹlu wa jù awọn ti o pẹlu rẹ̀ lọ:

8. Apa ẹran-ara li o pẹlu rẹ̀, ṣugbọn Oluwa Ọlọrun wa li o pẹlu wa lati ràn wa lọwọ, ati lati jà ogun wa. Awọn enia na si gbẹkẹ wọn le ọ̀rọ Hesekiah, ọba Juda.

9. Lẹhin eyi ni Sennakeribu, ọba Assiria, rán awọn iranṣẹ si Jerusalemu, (ṣugbọn on tikararẹ̀ dótì Lakiṣi ati gbogbo ogun rẹ̀ pẹlu rẹ̀) sọdọ Hesekiah, ọba Juda ati sọdọ gbogbo Juda ti o wà ni Jerusalemu wipe,

Ka pipe ipin 2. Kro 32