Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2. Kro 28:8-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

8. Awọn ọmọ Israeli si kó ọkẹ mẹwa ninu awọn arakunrin wọn ni igbekun lọ, awọn obinrin, awọn ọmọkunrin, ati awọn ọmọbinrin, nwọn si kó ikogun pupọ lọdọ wọn pẹlu, nwọn si mu ikogun na wá si Samaria.

9. Woli Oluwa kan si wà nibẹ, orukọ ẹniti ijẹ Odedi: o si jade lọ ipade ogun ti o wá si Samaria, o si wi fun wọn pe, Kiyesi i, nitoriti Oluwa Ọlọrun awọn baba nyin binu si Juda li on ṣe fi wọn le nyin lọwọ, ẹnyin si pa wọn ni ipa-oro ti o de òke ọrun.

10. Ati nisisiyi ẹnyin npete lati tẹ awọn ọmọ Juda ati Jerusalemu ba fun ẹrú-kunrin ati ẹrú-birin nyin: ẹnyin kò ha jẹbi Oluwa Ọlọrun nyin, ani ẹnyin?

11. Njẹ nitorina, ẹ gbọ́ temi, ki ẹ si jọwọ awọn igbekun ti ẹnyin ti kó ni igbekun ninu awọn arakunrin nyin lọwọ lọ: nitori ibinu kikan Oluwa mbẹ lori nyin.

12. Nigbana li awọn kan ninu awọn olori, awọn ọmọ Efraimu, Asariah, ọmọ Johanani, Berekiah, ọmọ Meṣillemoti, ati Jehiskiah, ọmọ Ṣallumu, ati Amasa, ọmọ Hadlai, dide si awọn ti o ti ogun na bọ̀.

Ka pipe ipin 2. Kro 28