Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1. Kro 12:4-19 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Ati Ismaiah ara Gibeoni, akọni ninu awọn ọgbọ̀n, ati lori ọgbọ̀n (enia) ati Jeremiah, ati Jahasieli, ati Johanani, ati Josabadi ara Gedera.

5. Elusai ati Jeremoti, ati Bealiah, ati Ṣemariah, ati Ṣefatiah ara Harofi,

6. Elkana, ati Jesiah, ati Asareelti ati Joeseri, ati Jaṣobeamu, awọn ara Kora,

7. Ati Joela, ati Sebadiah, awọn ọmọ Jerohamu ti Gedori.

8. Ati ninu awọn ara Gadi, awọn ọkunrin akọni kan ya ara wọn sọdọ Dafidi ninu iho ni iju, awọn ọkunrin ogun ti o yẹ fun ija ti o le di asà on ọ̀kọ mu, oju awọn ẹniti o dabi oju kiniun, nwọn si yara bi agbọnrin lori awọn òke nla;

9. Eseri ekini, Obadiah ekeji, Eliobu ẹkẹta,

10. Miṣmanna ẹkẹrin, Jeremiah ẹkarun,

11. Attai ẹkẹfa, Elieli ekeje,

12. Johanani ẹkẹjọ, Elsabadi ẹkẹsan,

13. Jeremiah ẹkẹwa, Makbanai ẹkọkanla.

14. Awọn wọnyi li awọn ọmọ Gadi, awọn olori ogun: ẹniti o kere jù to fun ọgọrun enia, ati ẹniti o pọ̀ju to fun ẹgbẹrun.

15. Wọnyi li awọn ti o gòke odò Jordani li oṣù ekini, nigbati o kún bò gbogbo bèbe rẹ̀; nwọn si le gbogbo awọn ti o wà li afonifoji ninu ila-õrùn, ati niha iwọ-õrùn.

16. Ninu awọn ọmọ Benjamini ati Juda si tọ Dafidi wá lori òke.

17. Dafidi si jade lọ ipade wọn, o si dahun o si wi fun wọn pe, Bi o ba ṣepe ẹnyin tọ̀ mi wá li alafia lati ràn mi lọwọ, ọkàn mi yio ṣọkan pẹlu nyin: ṣugbọn bi o ba ṣepe ẹnyin wá lati fi mi hàn fun awọn ọta mi, nigbati ẹbi kò si lọwọ mi, ki Ọlọrun awọn baba wa ki o wò o, ki o si ṣe idajọ.

18. Nigbana ni ẹmi bà lé Amasai, ti iṣe olori awọn ọgbọn na, wipe, Tirẹ li awa, Dafidi, tirẹ li a si nṣe, iwọ ọmọ Jesse: alafia! alafia ni fun ọ! alafia si ni fun awọn oluranlọwọ rẹ; nitori Ọlọrun rẹ ni nràn ọ lọwọ. Dafidi si gbà wọn, o si fi wọn jẹ olori ẹgbẹ-ogun.

19. Ninu ẹyà Manasse si ya si ọdọ Dafidi, nigbati o ba awọn ara Filistia wá lati ba Saulu jagun, ṣugbọn nwọn kò ràn wọn lọwọ: nitori awọn olori awọn ara Filistia, nigbati nwọn gbero, rán a lọ wipe, Ti on ti ori wa ni on o fi pada lọ si ọdọ Saulu oluwa rẹ̀.

Ka pipe ipin 1. Kro 12