Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Esek 36:15-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Bẹ̃ni emi kì yio mu ki enia gbọ́ ìtiju awọn keferi ninu rẹ mọ, bẹ̃ni iwọ kì yio rù ẹ̀gan awọn orilẹ-ède mọ, bẹ̃ni iwọ kì yio mu ki orilẹ-ẹ̀de rẹ ṣubu mọ, li Oluwa Ọlọrun wi.

16. Ọ̀rọ Oluwa si tọ̀ mi wá, wipe,

17. Ọmọ enia, nigbati ile Israeli ngbe ilẹ ti wọn; nwọn bà a jẹ nipa ọ̀na wọn, ati nipa iṣe wọn: ọ̀na wọn loju mi dabi aimọ́ obinrin ti a mu kuro.

18. Nitorina emi fi irúnu mi si ori wọn, nitori ẹ̀jẹ ti wọn ti ta sori ilẹ na, ati nitori ere wọn ti wọn ti fi bà a jẹ.

19. Emi si ti tú wọn ká sãrin awọn keferi, a si fọn wọn ká si gbogbo ilẹ: emi dá wọn lẹjọ, gẹgẹ bi ọ̀na wọn, ati gẹgẹ bi iṣe wọn.

20. Nigbati awọn si wọ̀ inu awọn keferi, nibiti nwọn lọ, nwọn bà orukọ mimọ́ mi jẹ, nigbati nwọn wi fun wọn pe, Awọn wọnyi li enia Oluwa, nwọn si ti jade kuro ni ilẹ rẹ̀.

Ka pipe ipin Esek 36