Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Esek 32:29-32 Yorùbá Bibeli (YCE)

29. Edomu wà nibẹ, awọn ọba rẹ̀, ati awọn ọmọ-alade rẹ̀, ti a tẹ́ pẹlu agbara wọn tì awọn ti a fi idà pa, nwọn o dubulẹ tì awọn alaikọlà, ati pẹlu awọn ti o sọkalẹ lọ si ihò.

30. Awọn ọmọ-alade ariwa wà nibẹ, gbogbo wọn, ati awọn ara Sidoni, ti nwọn sọkalẹ lọ pẹlu awọn ti a pa; pẹlu ẹ̀ru wọn, oju agbara wọn tì wọn; nwọn si dubulẹ li alaikọlà pẹlu awọn ti a fi idà pa, nwọn si rù itiju wọn pẹlu awọn ti o sọkalẹ lọ si ihò.

31. Farao yio ri wọn, a o si tù u ninu lori gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀, ani Farao ati gbogbo ogun rẹ̀ ti a fi idà pa, li Oluwa Ọlọrun wi.

32. Nitoriti emi ti dá ẹ̀ru mi silẹ ni ilẹ alãye: a o si tẹ́ ẹ si ãrin awọn alaikọlà, pẹlu awọn ti a fi idà pa ani Farao ati gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀, li Oluwa Ọlọrun wi.

Ka pipe ipin Esek 32