Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹk. Jer 4:5-17 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Awọn ti o ti njẹ ohun didùndidùn nkú lọ ni ita: awọn ti a ti tọ́ ninu aṣọ-òdodó, gbá ãtàn mọra.

6. Nitori aiṣedede ọmọbinrin awọn enia mi tobi jù ẹ̀ṣẹ Sodomu lọ, ti a bì ṣubu ni iṣẹju, laisi iṣiṣẹ ọwọ ninu rẹ̀.

7. Awọn Nasire rẹ̀ mọ́ jù ẹ̀gbọn-owu, nwọn funfun jù wàra; irisi wọn pọn jù iyùn, apẹrẹ wọn dabi okuta Safire:

8. Oju wọn dudu jù ẽdu nisisiyi; a kò mọ̀ wọn ni ita: àwọ wọn lẹ mọ egungun wọn; o di gbigbẹ gẹgẹ bi igi.

9. Awọn ti a fi idà pa san jù awọn ti a fi ebi pa, ti ndaku, ti a gún wọn lara nitori aisi eso-oko.

10. Ọwọ awọn obinrin alãnu ti sè awọn ọmọ awọn tikarawọn: awọn wọnyi li ohun jijẹ fun wọn ni igba wahala ọmọbinrin awọn enia mi.

11. Oluwa ti ṣe aṣepe irunu rẹ̀; o ti dà ibinu gbigbona rẹ̀ jade, o ti dá iná ni Sioni, ti o si ti jo ipilẹ rẹ̀ run.

12. Awọn ọba aiye, ati gbogbo olugbe ilẹ-aiye, kò gbagbọ pe aninilara ati ọta iba ti wọ inu ẹnu-bode Jerusalemu.

13. Nitori ẹ̀ṣẹ awọn woli rẹ̀, ati aiṣedede awọn alufa rẹ̀, ti nwọn ti ta ẹ̀jẹ awọn olododo silẹ li ãrin rẹ̀.

14. Nwọn ti rin kiri bi afọju ni ita, nwọn di alaimọ́ fun ẹ̀jẹ tobẹ̃ ti enia kò le fi ọwọ kan aṣọ wọn.

15. Nwọn nkigbe si wọn pe, ẹ lọ! alaimọ́ ni! ẹ lọ! ẹ lọ! ẹ máṣe fi ọwọ kan a! nigbati nwọn salọ, nwọn si rìn kiri pẹlu: nwọn nwi lãrin awọn orilẹ-ède pe, awọn kì o ṣatipo nibẹ mọ.

16. Oju Oluwa ti tú wọn ka: on kì o fiyesi wọn mọ: nwọn kò buyin fun awọn alufa, nwọn kò ṣãnu fun awọn àgbagba.

17. Bi o ṣe ti wa ni, oju wa nwọ̀na siwaju ati siwaju, fun iranlọwọ wa ti o jẹ asan: lori ile-iṣọ wa, awa nwọ̀na fun orilẹ-ède, ti kò le ràn ni lọwọ.

Ka pipe ipin Ẹk. Jer 4