Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Matiu 13:12-17 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Nítorí ẹni tí ó bá ní nǹkan, òun ni a óo tún fún sí i, kí ó lè ní ànító ati àníṣẹ́kù. Ẹni tí kò bá sì ní, a óo gba ìwọ̀nba díẹ̀ tí ó ní lọ́wọ́ rẹ̀.

13. Ìdí tí mo fi ń fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀ nìyí, nítorí wọ́n lajú sílẹ̀ ni, ṣugbọn wọn kò ríran. Wọ́n ní etí, ṣugbọn wọn kò gbọ́ràn, bẹ́ẹ̀ ni òye kò yé wọn.

14. Báyìí ni àsọtẹ́lẹ̀ Aisaya ṣe ṣẹ sí wọn lára, nígbà tí ó sọ pé.‘Ní ti gbígbọ́, ẹ óo gbọ́,ṣugbọn kò ní ye yín;ní ti pé kí ẹ ríran, ẹ óo wò títí,ṣugbọn ẹ kò ní rí nǹkankan.

15. Ọkàn àwọn eniyan yìí ti le,etí wọn ti di,wọ́n sì ti di ojú wọn.Kí wọn má baà fi ojú wọn ríran,kí wọn má baà fi etí wọn gbọ́ràn,kí wọn má baà mòye,kí wọn má baà yipada,kí n wá gbà wọ́n là.’

16. “Ṣugbọn ẹ̀yin ṣe oríire tí ojú yín ríran, tí etí yín sì gbọ́ràn.

17. Nítorí mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ dájúdájú pé, ọ̀pọ̀ àwọn wolii ati àwọn olódodo dàníyàn láti rí àwọn nǹkan tí ẹ̀ ń rí, ṣugbọn wọn kò rí wọn; wọ́n fẹ́ gbọ́ àwọn ohun tí ẹ̀ ń gbọ́ ṣugbọn wọn kò gbọ́.

Ka pipe ipin Matiu 13