Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 4:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ó ń kọ́ àwọn eniyan ninu àwọn ilé ìpàdé wọn. Gbogbo eniyan sì ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní rere.

16. Ó wá dé Nasarẹti, ìlú tí wọ́n ti tọ́ ọ dàgbà. Gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀, nígbà tí ó di ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sí ilé ìpàdé. Ó bá dìde láti ka Ìwé Mímọ́.

17. Wọ́n fún un ní ìwé wolii Aisaya. Nígbà tí ó ṣí i, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé,

18. “Ẹ̀mí Oluwa wà pẹlu minítorí ó ti fi òróró yàn míláti waasu ìyìn rere fún àwọn talaka.Ó rán mi láti waasu ìtúsílẹ̀fún àwọn tí wọ́n wà ní ìgbèkùn,ati láti mú kí àwọn afọ́jú ríran;láti jẹ́ kí àwọn tí a ni lára lọ ní alaafia,

19. ati láti waasu ọdún tí Oluwa yóo gba àwọn eniyan rẹ̀ là.”

Ka pipe ipin Luku 4