Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 19:38-42 BIBELI MIMỌ (BM)

38. Wọ́n ń wí pé,“Aláásìkí ni ẹni tí ó ń bọ̀ bí ọba ní orúkọ Oluwa.Alaafia ní ọ̀run! Ògo ní òkè ọ̀run!”

39. Àwọn kan tí wọ́n jẹ́ Farisi tí wọ́n wà láàrin àwọn eniyan sọ fún un pé, “Olùkọ́ni, bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”

40. Ó bá dá wọn lóhùn pé, “Mò ń sọ fun yín pé, bí àwọn wọnyi bá dákẹ́, àwọn òkúta yóo kígbe sókè.”

41. Nígbà tí wọ́n súnmọ́ etí ìlú, ó wo ìlú náà, ó bá bú sẹ́kún lórí rẹ̀.

42. Ó ní, “Ìbá ti dára tó lónìí, bí o bá mọ̀ lónìí ohun tí ó jẹ́ ọ̀nà alaafia rẹ! Ṣugbọn ó pamọ́ fún ọ.

Ka pipe ipin Luku 19