Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Aposteli 28:24-31 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Àwọn mìíràn gba ohun tí ó sọ gbọ́, ṣugbọn àwọn mìíràn kò gbàgbọ́.

25. Nígbà tí ohùn wọn kò dọ́gba láàrin ara wọn, wọ́n bá ń túká lọ. Paulu wá tún sọ gbolohun kan, ó ní, “Òtítọ́ ni Ẹ̀mí Mímọ́ sọ láti ẹnu wolii Aisaya sí àwọn baba-ńlá yín.

26. Ó ní,‘Lọ sọ fún àwọn eniyan yìí pé:Ẹ óo fetí yín gbọ́, ṣugbọn kò ní ye yín;Ẹ óo wò ó títí, ṣugbọn ẹ kò ní mọ̀ ọ́n.

27. Nítorí ọkàn àwọn eniyan yìí kò ṣí; wọ́n ti di alágbọ̀ọ́ya,wọ́n ti dijú.Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀,wọn ìbá fi ojú wọn ríran,wọn ìbá fetí gbọ́ràn,òye ìbá yé wọn,wọn ìbá yipada;èmi ìbá sì wò wọ́n sàn.’

28. “Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé a ti rán iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọrun yìí sí àwọn tí kì í ṣe Juu. Àwọn ní tiwọn yóo gbọ́.”

29. Nígbà tí Paulu ti sọ báyìí tán, àwọn Juu túká, wọ́n ń bá ara wọn jiyàn kíkankíkan.

30. Fún ọdún meji gbáko ni Paulu fi gbé ninu ilé tí ó gbà fúnra rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ó ń gba gbogbo àwọn tí ó ń wá rí i.

31. Ó ń waasu ìjọba Ọlọrun. Ó ń kọ́ àwọn eniyan nípa Oluwa Jesu Kristi láì bẹ̀rù ohunkohun. Ẹnikẹ́ni kò sì dí i lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Aposteli 28