Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Heberu 3:8-14 BIBELI MIMỌ (BM)

8. ẹ má ṣe agídí, gẹ́gẹ́ bíi ti àkókò ìṣọ̀tẹ̀,ní àkókò ìdánwò ninu aṣálẹ̀,

9. nígbà tí àwọn baba-ńlá yín dán mi wò,tí wọ́n fi rí iṣẹ́ mi fún ogoji ọdún.

10. Nítorí náà, mo bínú sí ìran wọn.Mo ní, ‘Nígbà gbogbo ni wọ́n máa ń ṣìnà ní ọkàn wọn.Iṣẹ́ mi kò yé wọn.’

11. Ni mo bá búra pẹlu ibinu,pé wọn kò ní dé ibi ìsinmi mi.”

12. Ẹ kíyèsára, ará, kí ó má ṣe sí ẹnikẹ́ni ninu yín tí yóo ní inú burúkú tóbẹ́ẹ̀ ti kò ní ní igbagbọ, tí yóo wá pada kúrò lẹ́yìn Ọlọrun alààyè.

13. Ṣugbọn ẹ máa gba ara yín níyànjú lojoojumọ níwọ̀n ìgbà tí ọ̀rọ̀ “Òní” tí Ìwé Mímọ́ sọ bá ti bá àwa náà wí, kí ẹ̀ṣẹ̀ má baà tan ẹnikẹ́ni lọ, kí ó sì mú kí ó ṣe agídí sí Ọlọrun.

14. Nítorí a ti di àwọn tí ó ń bá Kristi kẹ́gbẹ́ bí a bá fi ọkàn tán an títí dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti fi ọkàn tán an ní ìbẹ̀rẹ̀ igbagbọ wa.

Ka pipe ipin Heberu 3