Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Heberu 3:14-19 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Nítorí a ti di àwọn tí ó ń bá Kristi kẹ́gbẹ́ bí a bá fi ọkàn tán an títí dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti fi ọkàn tán an ní ìbẹ̀rẹ̀ igbagbọ wa.

15. Bí ó ti wà ní àkọsílẹ̀ pé,“Lónìí, bí ẹ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,ẹ má ṣe agídí gẹ́gẹ́ bíi ti àkókò ọ̀tẹ̀.”

16. Mò ń bèèrè, àwọn ta ni ó gbọ́ tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀? Ṣebí gbogbo àwọn tí wọ́n bá Mose jáde kúrò ní Ijipti ni.

17. Àwọn ta ni Ọlọrun bínú sí ní ogoji ọdún? Ṣebí àwọn tí ó ṣẹ̀ ni, tí òkú wọn wà káàkiri ní aṣálẹ̀.

18. Àwọn ta ni ó búra pé wọn kò ní wọ inú ìsinmi òun? Ṣebí àwọn aláìgbọràn ni.

19. A rí i pé wọn kò lè wọ inú ìsinmi yìí nítorí wọn kò gbàgbọ́.

Ka pipe ipin Heberu 3