Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Heberu 10:16-22 BIBELI MIMỌ (BM)

16. “Èyí ni majẹmu tí n óo bá wọn dánígbà tí ó bá yá, Èmi Oluwa ni mo sọ bẹ́ẹ̀,Èmi óo fi òfin mi sí ọkàn wọn,n óo kọ wọ́n sí àyà wọn.”

17. Ó tún ní, “N kò ní ranti ẹ̀ṣẹ̀ ati ìwà burúkú wọn mọ́.”

18. Nígbà tí a bá ti dárí àwọn nǹkan wọnyi ji eniyan, kò tún sí ìrúbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ mọ́.

19. Nítorí náà, ẹ̀yin ará, a ní ìgboyà láti wọ Ibi Mímọ́ jùlọ tí ó wà lẹ́yìn aṣọ ìkélé nípa ẹ̀jẹ̀ Jesu,

20. nípa ọ̀nà titun ati ọ̀nà ààyè tí ó ti yà sọ́tọ̀ fún wa tíí ṣe ẹran-ara rẹ̀.

21. A tún ní alufaa àgbà tí ó wà lórí ìdílé Ọlọrun.

22. Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí á súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pẹlu òtítọ́ ọkàn ati igbagbọ tí ó kún, kí á fi ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wẹ ọkàn wa mọ́, kí ó wẹ ẹ̀rí-ọkàn burúkú wa nù, kí á fi omi mímọ́ wẹ ara wa.

Ka pipe ipin Heberu 10