Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 22:1-10 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí OLUWA gba Dafidi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ati lọ́wọ́ Saulu, Dafidi kọ orin yìí sí OLUWA pé:

2. “OLUWA ni àpáta mi,ààbò mi, ati olùgbàlà mi;

3. Ọlọrun mi, àpáta mi,ọ̀dọ̀ ẹni tí mo sá pamọ́ sí.Àpáta mi ati ìgbàlà mi,ààbò mi ati ibi ìpamọ́ mi,olùgbàlà mi, ìwọ ni o gbà mí lọ́wọ́ ìwà ipá.

4. Mo ké pe OLUWA, ẹni tí ìyìn yẹ,Ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

5. “Ikú yí mi káàkiri, bí ìgbì omi;ìparun sì bò mí mọ́lẹ̀ bíi ríru omi;

6. isà òkú ya ẹnu sílẹ̀ dè mí,ewu ikú sì dojú kọ mí.

7. Ninu ìpọ́njú mi, mo ké pe OLUWAmo ké pe Ọlọrun mi,ó gbọ́ ohùn mi láti inú tẹmpili rẹ̀;ó sì tẹ́tí sí igbe mi.

8. “Ayé mì, ó sì wárìrì;ìpìlẹ̀ àwọn ọ̀run sì wárìrì,ó mì tìtì, nítorí ibinu Ọlọrun.

9. Èéfín jáde láti ihò imú rẹ̀,iná ajónirun sì jáde láti ẹnu rẹ̀;ẹ̀yinná tí ó pọ́n rẹ̀rẹ̀ ń ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ jáde.

10. Ó tẹ àwọn ọ̀run ba, ó sì sọ̀kalẹ̀;ìkùukùu tí ó ṣókùnkùn sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 22