Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sakaraya 11:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ṣílẹ̀kùn rẹ, ìwọ ilẹ̀ Lẹbanonikí iná lè jó àwọn igi kedari rẹ!

2. Ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin igi Sipirẹsi,nítorí igi kedari ti ṣubú,àwọn igi ológo ti parun.Ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin igi oaku ní Baṣani,nítorí pé, a ti gé àwọn igi igbó dídí Baṣani lulẹ̀!

3. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, kí ẹ gbọ́ ẹkún àwọn darandaran,nítorí ògo wọn ti díbàjẹ́.Ẹ gbọ́ bí àwọn kinniun ti ń bú ramúramù,nítorí igbó tí wọn ń gbélẹ́bàá odò Jọdani ti parun!

4. Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA, Ọlọrun mi sọ; ó ní, “Fi ara rẹ sí ipò olùṣọ́-aguntan tí ó da àwọn ẹran rẹ̀ lọ sí ibi tí wọ́n ti pa wọ́n.

5. Àwọn tí wọ́n rà wọ́n pa wọ́n ní àpagbé; àwọn tí wọn n tà wọ́n sì wí pé, ‘Ìyìn ni fún OLUWA, mo ti di ọlọ́rọ̀’; àwọn tí wọ́n ni wọ́n kò tilẹ̀ ṣàánú wọn.”

6. OLUWA ní, “Bẹ́ẹ̀ gan-an ni n kò ní ṣàánú àwọn eniyan ilẹ̀ yìí mọ́. Fúnra mi ni n óo fi wọ́n lé àwọn aláṣẹ ati àwọn ọba wọn lọ́wọ́. Wọn óo run ilẹ̀ náà, n kò sì ní gba ẹnikẹ́ni lọ́wọ́ wọn.”

7. Mo ti di darandaran agbo ẹran tí à ń dà lọ fún àwọn alápatà. Mo mú ọ̀pá meji, mo sọ ọ̀kan ní “Oore-ọ̀fẹ́,” mo sì sọ ekeji ní “Ìṣọ̀kan.”

Ka pipe ipin Sakaraya 11