Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Rutu 4:14-22 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Àwọn obinrin bá sọ fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún OLUWA, tí kò ṣe ọ́ ní aláìní ìbátan, kí OLUWA ṣe ọmọ náà ní olókìkí ní Israẹli.

15. Ọmọ yìí yóo mú kí adùn ayé rẹ sọjí, yóo sì jẹ́ olùtọ́jú fún ọ ní ọjọ́ ogbó rẹ, nítorí iyawo ọmọ rẹ tí ó fẹ́ràn rẹ, tí ó sì ju ọmọkunrin meje lọ ni ó bímọ fún ọ.”

16. Naomi bá gba ọmọ náà, ó tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì di olùtọ́jú rẹ̀.

17. Àwọn obinrin àdúgbò bá sọ ọmọ náà ní Obedi, wọ́n ń sọ káàkiri pé, “A bí ọmọkunrin kan fún Naomi.” Obedi yìí ni baba Jese tíí ṣe baba Dafidi.

18. Àwọn atọmọdọmọ Peresi nìwọ̀nyí: Peresi ni baba Hesironi;

19. Hesironi bí Ramu, Ramu bí Aminadabu;

20. Aminadabu bí Naṣoni; Naṣoni bí Salimoni;

21. Salimoni bí Boasi, Boasi bí Obedi;

22. Obedi bí Jese, Jese sì bí Dafidi.

Ka pipe ipin Rutu 4