Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 45:3-12 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Sán idà rẹ mọ́ ìdí, ìwọ alágbára,ninu ògo ati ọlá ńlá rẹ.

4. Máa gun ẹṣin ìṣẹ́gun lọ ninu ọlá ńlá rẹ,máa jà fún òtítọ́ ati ẹ̀tọ́,kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ fún ọ ní ìṣẹ́gun ńlá.

5. Àwọn ọfà rẹ mú, wọ́n gún àwọn ọ̀tá ọba lọ́kàn,àwọn eniyan ń wó lulẹ̀ níwájú rẹ.

6. Ìjọba tí Ọlọrun fún ọ wà lae ati laelae.Ọ̀pá àṣẹ rẹ, ọ̀pá àṣẹ ẹ̀tọ́ ni.

7. O fẹ́ràn òdodo, o sì kórìíra ìwà ìkànítorí náà ni Ọlọrun, àní Ọlọrun rẹ, ṣe fi àmì òróró yàn ọ́.Àmì òróró ayọ̀ ni ó fi gbé ọ gaju àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ lọ.

8. Aṣọ rẹ kún fún òórùn oríṣìíríṣìí turari,láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ni wọ́n tí ń fi ohun èlò ìkọrin olókùn dá ọ lára yá.

9. Àwọn ọmọ ọba wà lára àwọn obinrin inú àgbàlá rẹ,ayaba dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ,ó fi ojúlówó wúrà ṣe ọ̀ṣọ́ sára.

10. Gbọ́, ìwọ ọmọbinrin, ronú kí o sì tẹ́tí sílẹ̀,gbàgbé àwọn eniyan rẹ ati ilé baba rẹ;

11. ẹwà rẹ yóo sì mú ọ wu ọba;òun ni oluwa rẹ, nítorí náà bu ọlá fún un.

12. Àwọn ará Tire yóo máa fi ẹ̀bùn wá ojurere rẹ,àní, àwọn eniyan tí wọ́n ní ọrọ̀ jùlọ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 45