Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 37:3-15 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA; kí o sì máa ṣe rere.Máa gbe ilẹ̀ náà; ewu kò sì ní wu ọ́.

4. Jẹ́ kí inú rẹ máa dùn ninu OLUWA;yóo sì fún ọ ní ohun tí ọkàn rẹ ń fẹ́.

5. Fi ọ̀nà rẹ lé OLUWA lọ́wọ́;gbẹ́kẹ̀lé e, yóo sì ṣe ohun tí ó yẹ.

6. Yóo mú kí ìdáláre rẹ tàn bí ìmọ́lẹ̀;ẹ̀tọ́ rẹ yóo sì hàn kedere bí ọ̀sán gangan.

7. Dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú OLUWA; fi sùúrù gbẹ́kẹ̀lé e.Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí ẹni tí nǹkan ń dára fún;tabi nítorí ẹni tí ń gbèrò ibi, tí ó sì ń ṣe é.

8. Yẹra fún ibinu; sì yàgò fún ìrúnú.Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná; ibi ni àyọrísí rẹ̀.

9. Nítorí pé a óo pa àwọn eniyan burúkú run;ṣugbọn àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWAni yóo jogún ilẹ̀ náà.

10. Ẹ fún eniyan burúkú ní ìgbà díẹ̀ sí i, yóo pòórá;ẹ̀ báà wá a títí ní ààyè rẹ̀, kò ní sí níbẹ̀.

11. Ṣugbọn àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ ni yóo jogún ilẹ̀ náà:wọn óo máa gbádùn ara wọn;wọn óo sì ní alaafia lọpọlọpọ.

12. Eniyan burúkú dìtẹ̀ mọ́ olódodo;ó sì ń wò ó bíi kíkú bíi yíyè.

13. Ṣugbọn OLUWA ń fi eniyan burúkú rẹ́rìn-ín,nítorí ó mọ̀ pé ọjọ́ ìparun rẹ̀ ń bọ̀.

14. Àwọn eniyan burúkú fa idà yọ, wọ́n sì kẹ́ ọfà wọnláti gba ẹ̀mí talaka ati aláìní,láti pa àwọn tí ń rìn lọ́nà ẹ̀tọ́.

15. Ṣugbọn idà wọn ni o óo fi pa wọ́n,ọrun wọn yóo sì dá.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 37