Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 28:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ìwọ ni mo kígbe pè, OLUWA,ìwọ ni ààbò mi, má di etí sí mi.Nítorí bí o bá dákẹ́ sí min óo dàbí àwọn òkú, tí wọ́n ti lọ sinu kòtò.

2. Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi,bí mo ti ń kígbe sí ọ pé kí o ràn mí lọ́wọ́;tí mo gbé ọwọ́ mi sókèsí ìhà ilé mímọ́ rẹ.

3. Má ṣe kó mi lọ pẹlu àwọn eniyan burúkú,pẹlu àwọn tí ń ṣe iṣẹ́ ibi,àwọn tí ń bá àwọn aládùúgbò wọnsọ ọ̀rọ̀ alaafia,ṣugbọn tí ètekéte ń bẹ ninu ọkàn wọn.

4. San án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,àní gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ burúkú wọn;san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,fún wọn ní èrè tí ó tọ́ sí wọn.

5. Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ OLUWA sí,wọn kò sì bìkítà fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀,OLUWA yóo sọ wọ́n di ilẹ̀,kò sì ní gbé wọn dìde mọ́.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 28