Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 114:1-8 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti,tí àwọn ọmọ Jakọbu jáde kúrò láàrin àwọn tí ń sọ èdè àjèjì,

2. Juda di ilé mímọ́ rẹ̀,Israẹli sì di ìjọba rẹ̀.

3. Òkun rí i, ó sá,Jọdani rí i, ó pada sẹ́yìn.

4. Àwọn òkè ńláńlá ń fò bí àgbò,àwọn òkè kéékèèké ń fò bí ọmọ aguntan.

5. Kí ló dé, tí o fi sá, ìwọ òkun?Kí ló ṣẹlẹ̀ tí o fi pada sẹ́yìn, ìwọ Jọdani?

6. Ẹ̀yin òkè ńlá, kí ló dé tí ẹ fi fò bí àgbò?Ẹ̀yin òkè kéékèèké, kí ló ṣẹlẹ̀ tí ẹ fi fò bí ọmọ aguntan?

7. Wárìrì níwájú OLUWA, ìwọ ilẹ̀,wárìrì níwájú Ọlọrun Jakọbu.

8. Ẹni tí ó sọ àpáta di adágún omi,tí ó sì sọ akọ òkúta di orísun omi.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 114