Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 3:14-26 BIBELI MIMỌ (BM)

14. OLUWA sọ fún Mose ninu aṣálẹ̀ Sinai, ó ní,

15. “Ka iye àwọn ọmọkunrin Lefi gẹ́gẹ́ bí ìdílé baba wọn. Bẹ̀rẹ̀ láti ọmọ oṣù kan lọ sókè.”

16. Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún un.

17. Lefi ní ọmọkunrin mẹta: Geriṣoni, Kohati ati Merari, wọ́n sì jẹ́ olórí àwọn ìdílé wọn.

18. Orúkọ àwọn ọmọ Geriṣoni ni Libini ati Ṣimei.

19. Orúkọ àwọn ọmọ Kohati ni Amramu, Iṣari, Heburoni ati Usieli.

20. Orúkọ àwọn ọmọ Merari ni Mahili ati Muṣi. Àwọn ìdílé Lefi nìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.

21. Geriṣoni ni baba ńlá àwọn ọmọ Libini ati àwọn ọmọ Ṣimei.

22. Gbogbo àwọn ọkunrin tí a kà ninu wọn, láti ọmọ oṣù kan sókè jẹ́ ẹgbaarin ó dín ẹẹdẹgbẹta (7,500).

23. Àwọn ọmọ Geriṣoni yóo pàgọ́ tiwọn sẹ́yìn Àgọ́ Àjọ ní ìhà ìwọ̀ oòrùn.

24. Eliasafu ọmọ Laeli ni yóo jẹ́ olórí wọn.

25. Àwọn ni yóo máa ṣe ìtọ́jú ibi mímọ́ ati Àgọ́ Àjọ, aṣọ ìbòrí rẹ̀, ati aṣọ tí wọ́n ń ta sí ẹnu ọ̀nà àbáwọlé rẹ̀;

26. aṣọ tí wọ́n ń ta sí àgbàlá, aṣọ tí wọ́n ń ta sí ẹnu ọ̀nà àbáwọ àgbàlá tí ó yí ibi mímọ́ ati pẹpẹ ká, ati okùn, ati gbogbo nǹkan tí wọ́n ń lò pẹlu rẹ̀.

Ka pipe ipin Nọmba 3