Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 24:5-14 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Báwo ni àgọ́ rẹ ti dára tó ìwọ Jakọbu,ati ibùdó rẹ ìwọ Israẹli!

6. Ó dàbí àfonífojì tí ó tẹ́ lọ bẹẹrẹ,bí ọgbà tí ó wà lẹ́bàá odò.Ó dàbí àwọn igi aloe tí OLUWA gbìn,ati bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.

7. Òjò yóo rọ̀ fún Israẹli ní àkókò rẹ̀,omi yóo jáde láti inú agbè rẹ̀;àwọn ohun ọ̀gbìn rẹ̀ yóo sì rí omi mu.Ọba wọn yóo lókìkí ju Agagi lọ,ìjọba rẹ̀ ni a óo sì gbéga.

8. Ọlọrun kó wọn ti Ijipti wá,ó jà fún wọn gẹ́gẹ́ bí àgbáǹréré.Wọn yóo pa àwọn ọ̀tá wọn run,wọn óo wó egungun wọn, wọn óo sì fi ọfà pa wọ́n.

9. Ó dùbúlẹ̀, ó ba bíi kinniun,bí abo kinniun tí ó sùn, ta ló lè jí i dìde?Ibukun ni fún ẹni tí ó bá súre fún Israẹli,ẹni tí ó bá sì gbé Israẹli ṣépè, olúwarẹ̀ gbé!”

10. Balaki bá bínú sí Balaamu gidigidi, ó bẹ̀rẹ̀ sí fi ọwọ́ lu ọwọ́. Ó sì sọ fún Balaamu pé: “Mo pè ọ́ pé kí o wá gbé àwọn ọ̀tá mi ṣépè, ṣugbọn dípò kí o gbé wọ́n ṣépè, o súre fún wọn ní ìgbà mẹta!

11. Nítorí náà máa lọ sí ilé rẹ. Mo ti pinnu láti sọ ọ́ di eniyan pataki tẹ́lẹ̀ ni, ṣugbọn OLUWA ti dí ọ lọ́nà.”

12. Balaamu bá dáhùn pé: “Ṣebí mo ti sọ fún àwọn oníṣẹ́ tí o rán wá pé,

13. bí o tilẹ̀ fún mi ní ààfin rẹ, tí ó sì kún fún fadaka ati wúrà, sibẹsibẹ, n kò ní agbára láti ṣe ohunkohun ju ohun tí OLUWA bá sọ lọ. N kò lè dá ṣe rere tabi burúkú ní agbára mi, ohun tí OLUWA bá sọ ni n óo sọ.”

14. Balaamu tún sọ fún Balaki pé, “Èmi ń lọ sí ilé mi, ṣugbọn jẹ́ kí n kìlọ̀ fún ọ nípa ohun tí àwọn eniyan wọnyi yóo ṣe sí àwọn eniyan rẹ ní ẹ̀yìn ọ̀la.”

Ka pipe ipin Nọmba 24