Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nahumu 3:2-9 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Pàṣán ń ró, ẹṣin ń yan,kẹ̀kẹ́ ogun ń pariwo!

3. Àwọn ẹlẹ́ṣin ti múra ìjàpẹlu idà ati ọ̀kọ̀ tí ń kọ mànà.Ọpọlọpọ ni wọ́n ti pa sílẹ̀,òkítì òkú kúnlẹ̀ lọ kítikìti;òkú sùn lọ bẹẹrẹ láìníye,àwọn eniyan sì ń kọlu àwọn òkúbí wọn tí ń lọ!

4. Nítorí ọpọlọpọ ìwà àgbèrè Ninefe,tí wọ́n fanimọ́ra,ṣugbọn tí wọ́n kún fún òògùn olóró,ni gbogbo ìjìyà yìí ṣe dé bá a;nítorí ó ń fi ìwà àgbèrè rẹ̀ tan àwọn orílẹ̀-èdè jẹ,ó sì ń fi òògùn rẹ̀ mú àwọn eniyan.

5. OLUWA àwọn ọmọ ogun ní:“Wò ó! Mo ti gbógun tì ọ́, Ninefe,n óo ká aṣọ kúrò lára rẹ, n óo fi bò ọ́ lójú;n óo tú ọ sí ìhòòhò lójú àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn.Àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn yóo rí ìhòòhò rẹojú yóo sì tì ọ́.

6. N óo mú ẹ̀gbin bá ọ n óo fi àbùkù kàn ọ́;n óo sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà ati ẹni àpéwò.

7. Ẹnu yóo ya gbogbo àwọn tí ó bá wò ọ́, wọn yóo máawí pé: ‘Ninefe ti di ahoro; ta ni yóo dárò rẹ̀?Níbo ni n óo ti rí olùtùnú fún ọ?’ ”

8. Ṣé ìwọ Ninefe sàn ju ìlú Tebesi lọ, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ odò Naili, tí omi yíká, tí ó fi òkun ṣe ààbò, tí ó sì fi omi ṣe odi rẹ̀?

9. Etiopia ati Ijipti ni agbára rẹ̀ tí kò lópin; Puti ati Libia sì ni olùrànlọ́wọ́ rẹ̀.

Ka pipe ipin Nahumu 3