Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 29:23-30 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ OLUWA gẹ́gẹ́ bí ọba, dípò Dafidi, baba rẹ̀. Solomoni ní ìlọsíwájú, gbogbo àwọn eniyan Israẹli sì ń gbọ́ tirẹ̀.

24. Gbogbo àwọn ìjòyè, àwọn alágbára, ati gbogbo àwọn ọmọ Dafidi ọba ni wọ́n jẹ́jẹ̀ẹ́ láti máa gbọ́ ti Solomoni.

25. OLUWA gbé Solomoni ga lójú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fún un ní ọlá ju gbogbo àwọn ọba tí wọ́n ti jẹ ṣáájú rẹ̀ ní Israẹli.

26. Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi, ọmọ Jese, ṣe jọba lórí gbogbo Israẹli.

27. Ó jọba fún ogoji ọdún; ó jọba fún ọdún meje ní Heburoni, ó sì jọba fún ọdún mẹtalelọgbọn ní Jerusalẹmu.

28. Ẹ̀mí rẹ̀ gùn, ó lọ́rọ̀, ó sì lọ́lá, ó sì di arúgbó kàngẹ́kàngẹ́ kí ó tó kú, Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

29. Ìtàn ìgbé ayé ọba Dafidi láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin ni a kọ sí inú ìwé ìtàn tí wolii Samuẹli kọ, èyí tí wolii Natani kọ, ati èyí tí wolii Gadi kọ.

30. Àkọsílẹ̀ yìí sọ bí ó ti ṣe ìjọba rẹ̀, bí agbára rẹ̀ ti tó; ati gbogbo nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀ sí i, ati èyí tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli ati sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wà ní àyíká wọn.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 29