Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 29:21-26 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Ní ọjọ́ keji, wọ́n fi ẹgbẹrun akọ mààlúù rú ẹbọ sísun sí OLUWA, ati ẹgbẹrun àgbò, ati ẹgbẹrun ọ̀dọ́ aguntan, pẹlu ọrẹ ohun mímu ati ọpọlọpọ ẹbọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.

22. Wọ́n jẹ, wọ́n sì mu níwájú Ọlọrun ní ọjọ́ náà pẹlu ayọ̀ ńlá.Wọ́n tún fi Solomoni, ọmọ Dafidi, jẹ ọba lẹẹkeji. Wọ́n fi òróró yàn án ní ọba ní orúkọ OLUWA, Sadoku sì ni alufaa.

23. Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ OLUWA gẹ́gẹ́ bí ọba, dípò Dafidi, baba rẹ̀. Solomoni ní ìlọsíwájú, gbogbo àwọn eniyan Israẹli sì ń gbọ́ tirẹ̀.

24. Gbogbo àwọn ìjòyè, àwọn alágbára, ati gbogbo àwọn ọmọ Dafidi ọba ni wọ́n jẹ́jẹ̀ẹ́ láti máa gbọ́ ti Solomoni.

25. OLUWA gbé Solomoni ga lójú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fún un ní ọlá ju gbogbo àwọn ọba tí wọ́n ti jẹ ṣáájú rẹ̀ ní Israẹli.

26. Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi, ọmọ Jese, ṣe jọba lórí gbogbo Israẹli.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 29