Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 17:7-10 BIBELI MIMỌ (BM)

7. “Nítorí náà, sọ fún un pé, èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ‘mo mú un wá láti inú pápá, níbi tí ó ti ń da ẹran, pé kí ó wá jọba lórí, àwọn eniyan mi, Israẹli.

8. Mo sì ń wà pẹlu rẹ̀ ní gbogbo ibi tí ó ń lọ, mo sì ti pa àwọn ọ̀tá rẹ̀ run níwájú rẹ̀, n óo sì gbé orúkọ rẹ̀ ga bí orúkọ àwọn eniyan ńlá ayé.

9. N óo yan ibìkan fún Israẹli, àwọn eniyan mi, n óo fìdí wọn múlẹ̀, wọn óo máa gbé ilẹ̀ wọn, ẹnikẹ́ni kò ní yọ wọ́n lẹ́nu mọ́, àwọn ìkà kò tún ní ṣe wọ́n lófò mọ́ bíi ti àtijọ́,

10. nígbà tí mo ti yan àwọn adájọ́ láti darí Israẹli, àwọn eniyan mi. N óo tẹ orí àwọn ọ̀tá wọn ba. Bákan náà, èmi OLUWA ṣe ìlérí pe n óo fi ìdí ìdílé rẹ̀ múlẹ̀.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 17