Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 17:13-21 BIBELI MIMỌ (BM)

13. N óo jẹ́ baba fún un, yóo sì jẹ́ ọmọ fún mi. N kò ní yẹ ìfẹ́ ńlá mi tí mo ní sí i, bí mo ti yẹ ti Saulu, tí ó ṣáájú rẹ̀.

14. N óo fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ ní ilé mi ati ninu ìjọba mi títí lae. N óo sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.’ ”

15. Gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ni Natani sọ fún Dafidi, gẹ́gẹ́ bí ó ti rí i lójú ìran.

16. Dafidi bá lọ jókòó níwájú OLUWA, ó gbadura báyìí pé, “Kí ni èmi ati ilé mi jẹ́, tí o fi gbé mi dé ipò tí mo dé yìí?

17. Gbogbo èyí kò sì tó nǹkan lójú rẹ, Ọlọrun, o tún ṣèlérí nípa ìdílé èmi iranṣẹ rẹ fún ọjọ́ iwájú, o sì ti fi bí àwọn ìran tí ń bọ̀ yóo ti rí hàn mí, OLUWA Ọlọrun!

18. Kí ni mo tún lè sọ nípa iyì tí o bù fún èmi, iranṣẹ rẹ? Nítorí pé o mọ èmi iranṣẹ rẹ.

19. OLUWA, nítorí ti èmi iranṣẹ rẹ, ati gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni o fi ṣe àwọn nǹkan ńlá wọnyi, tí o sì fi wọ́n hàn.

20. Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ, OLUWA, kò sì sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn rẹ, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a ti fi etí wa gbọ́.

21. Ní gbogbo ayé, orílẹ̀-èdè wo ni ó tún dàbí Israẹli, àwọn eniyan rẹ, tí ìwọ Ọlọrun rà pada láti jẹ́ eniyan rẹ, tí o sì sọ orúkọ rẹ̀ di ńlá nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu tí o ṣe nígbà tí ó lé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn eniyan rẹ, tí o rà pada láti ilẹ̀ Ijipti?

Ka pipe ipin Kronika Kinni 17