Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 16:15-27 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Kò ní í gbàgbé majẹmu rẹ̀ títí lae,àní àwọn ohun tí ó ti pa láṣẹ láti ṣe fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,

16. majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó ti ṣe fún Isaaki,

17. tí ó sì ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu Jakọbu,gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ohun tí yóo wà títí lae,

18. ó ní, “Ẹ̀yin ni n óo fún ní ilẹ̀ Kenaani,bí ohun ìní yín, tí ẹ óo jogún.”

19. Nígbà tí wọn kò tíì pọ̀ pupọ,tí wọn kò sì jẹ́ nǹkan,tí wọ́n jẹ́ àjèjì níbẹ̀,

20. tí wọn ń lọ káàkiri láti orílẹ̀-èdè kan dé ekeji,láti ìjọba kan sí òmíràn,

21. kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ni wọ́n lára,ó bá àwọn ọba wí nítorí wọn.

22. Ó ní, “Ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi,ẹ má sì pa àwọn wolii mi lára!”

23. Ẹ kọrin sí OLUWA, gbogbo ayé!Ẹ máa kéde ìgbàlà rẹ̀ lojoojumọ.

24. Ẹ kéde ògo rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,ẹ polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrin àwọn eniyan!

25. OLUWA tóbi, ìyìn tọ́ sí i lọpọlọpọó sì yẹ kí á bọ̀wọ̀ fún un ju gbogbo àwọn oriṣa lọ.

26. Nítorí pé ère lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù sọ di ọlọrun,ṣugbọn OLUWA ló dá ọ̀run.

27. Ògo ati agbára yí i ká,ayọ̀ ati ìyìn sì kún Tẹmpili rẹ̀.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 16