Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Keji 9:6-17 BIBELI MIMỌ (BM)

6. N kò gba ohun tí wọ́n sọ fún mi gbọ́ títí tí mo fi dé ìhín, tí èmi gan-an sì fi ojú ara mi rí i. Ohun tí wọ́n sọ fún mi kò tó ìdajì ọgbọ́n rẹ, ohun tí mo rí yìí pọ̀ ju ohun tí wọ́n sọ fún mi lọ.

7. Àwọn iyawo rẹ ṣoríire. Àwọn òṣìṣẹ́ rẹ tí wọ́n wà lọ́dọ̀ rẹ nígbà gbogbo tí wọn ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ọgbọ́n rẹ náà ṣoríire.

8. Ògo ni fún OLUWA Ọlọrun rẹ, tí inú rẹ̀ dùn sí ọ, tí ó gbé ọ gorí oyè láti jọba ní orúkọ rẹ̀. Ó ní ìfẹ́ sí Israẹli, ó fẹ́ fi ìdí wọn múlẹ̀ títí lae; nítorí náà, ó fi ọ́ jọba lórí wọn, láti máa ṣe ìdájọ́ òtítọ́ ati òdodo.”

9. Ó fún ọba ní àwọn ẹ̀bùn wọnyi tí ó mú wá: ọgọfa (120) ìwọ̀n talẹnti wúrà, ọpọlọpọ turari olóòórùn dídùn ati ohun ọ̀ṣọ́ òkúta olówó iyebíye. Kò tún sí irú turari tí ọbabinrin yìí mú wá fún Solomoni ọba mọ́.

10. Àwọn iranṣẹ Huramu ati àwọn iranṣẹ Solomoni tí wọ́n mú wúrà wá láti Ofiri, tún mú igi aligumu ati àwọn òkúta olówó iyebíye wá pẹlu.

11. Igi aligumu yìí ni ọba fi ṣe àtẹ̀gùn láti máa gòkè ati láti máa sọ̀kalẹ̀ ninu tẹmpili OLUWA ati ninu ààfin ọba. Ó tún fi ṣe dùùrù ati hapu fún àwọn akọrin. Kò sí irú wọn rí ní gbogbo ilẹ̀ Juda.

12. Solomoni ọba fún ọbabinrin náà ní gbogbo ohun tí ọkàn rẹ̀ ń fẹ́. Ẹ̀bùn tí ó fún un ju èyí tí òun alára mú wá lọ. Lẹ́yìn náà ọbabinrin náà pada lọ sí ìlú rẹ̀.

13. Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni ń rí ní ọdọọdún jẹ́ ọtalelẹgbẹta ó lé mẹfa (666) talẹnti (kilogiramu 23,000),

14. láìka èyí tí àwọn oníṣòwò ati àwọn ọlọ́jà ń mú wá. Àwọn ọba Arabia ati àwọn gomina àwọn agbègbè ìjọba rẹ̀ náà a máa mú wúrà ati fadaka wá fún un.

15. Solomoni fi wúrà tí a fi òòlù lù ṣe igba (200) apata ńláńlá. Ìwọ̀n wúrà tí ó lò fún ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbẹta (600) ṣekeli.

16. Ó tún fi wúrà tí a fi òòlù lù ṣe ọọdunrun (300) apata kéékèèké. Ìwọ̀n wúrà tí ó lò fún ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ọọdunrun (300) ṣekeli. Ọba kó wọn sí ààfin Igbó Lẹbanoni.

17. Ọba fi eyín erin ṣe ìtẹ́ ńlá kan, ó sì yọ́ ojúlówó wúrà bò ó.

Ka pipe ipin Kronika Keji 9