1. Solomoni ọba ní,“OLUWA, o ti sọ pé o óo máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
2. Ṣugbọn nisinsinyii, mo ti kọ́ ilé kan tí ó lógo fún ọ,ibi tí o óo máa gbé títí lae.”
3. Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli wà níbẹ̀, ọba bá yíjú pada sí wọn, ó sì gbadura fún wọn.
4. Lẹ́yìn náà, ó ní, “Ẹni ìyìn ni OLUWA Ọlọrun Israẹli, tí ó mú ohun gbogbo tí ó wí fún Dafidi, baba mi, ṣẹ fúnrarẹ̀, nítorí ó wí pé,