Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Joẹli 3:8-16 BIBELI MIMỌ (BM)

8. N óo ta àwọn ọmọ yín ọkunrin ati àwọn ọmọ yín obinrin lẹ́rú fún àwọn ará Juda. Wọn yóo sì tà wọ́n fún àwọn ará Sabea, orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà réré; nítorí OLUWA ni ó sọ bẹ́ẹ̀.”

9. Ẹ kéde èyí láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè.Ẹ múra ogun,ẹ rú àwọn akọni sókè.Kí gbogbo àwọn ọmọ ogun súnmọ́ tòsí,ogun yá!

10. Ẹ fi irin ọkọ́ yín rọ idà,ẹ fi dòjé yín rọ ọ̀kọ̀,kí àwọn tí wọn kò lágbára wí pé, “Ọmọ ogun ni mí.”

11. Ẹ yára, ẹ wá,gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè tí ẹ wà ní àyíká,ẹ parapọ̀ níbẹ̀.Rán àwọn ọmọ ogun rẹ wá, OLUWA.

12. Jẹ́ kí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè dìde,kí wọ́n wá sí àfonífojì Jehoṣafati,nítorí níbẹ̀ ni n óo ti ṣe ìdájọ́ gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká.

13. Ẹ ti dòjé bọ oko, nítorí àkókò ìkórè ti tó,ẹ lọ fún ọtí waini nítorí ibi ìfúntí ti kún.Ìkòkò ọtí ti kún àkúnwọ́sílẹ̀,nítorí ìkà wọ́n pọ̀.

14. Ogunlọ́gọ̀ wà ní àfonífojì ìdájọ́,nítorí ọjọ́ OLUWA kù sí dẹ̀dẹ̀ níbẹ̀.

15. Oòrùn ati òṣùpá ti ṣókùnkùn,àwọn ìràwọ̀ kò sì tan ìmọ́lẹ̀ mọ́.

16. OLUWA kígbe láti Sioni,ó sọ̀rọ̀ láti Jerusalẹmu;ọ̀run ati ayé mì tìtì,ṣugbọn OLUWA ni ààbò fún àwọn eniyan rẹ̀,òun ni ibi ààbò fún Israẹli.

Ka pipe ipin Joẹli 3