Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Joẹli 2:4-18 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ìrísí wọn dàbí ìrísí ẹṣin,wọ́n sì ń sáré bí ẹṣin tí ń lọ ojú ogun.

5. Ìró wọn dàbí ìró kẹ̀kẹ́ ogun,wọ́n ń bẹ́ lórí àwọn òkè ńlá.Ìró wọn dàbí ìró iná tí ń jó pápá,bí ìgbà tí àwọn alágbára ọmọ ogun múra fún ogun.

6. Ìdààmú bá àwọn orílẹ̀-èdè tí ó bá ti fojú kàn wọ́n,gbogbo ọkàn á rẹ̀wẹ̀sì.

7. Wọ́n ń sáré bí akọni,wọ́n ń fo ògiri bí ọmọ ogun.Wọ́n tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́,ẹnikẹ́ni kò sì yà kúrò ní ọ̀nà tirẹ̀.

8. Wọn kò fi ara gbún ara wọn,olukuluku ń lọ ní ọ̀nà tirẹ̀;wọ́n kọlu àwọn nǹkan ààbò láìní ìdádúró.

9. Wọ́n ń gun odi ìlú,wọ́n ń sáré lórí odi.Wọ́n ń gun orí ilé wọlé,wọ́n gba ojú fèrèsé bẹ́ sinu ọ̀dẹ̀dẹ̀ bí olè.

10. Ilẹ̀ ń mì tìtì níwájú wọn,ọ̀run sì ń wárìrì,oòrùn, òṣùpá ati àwọn ìràwọ̀ ṣókùnkùn.

11. OLUWA sọ̀rọ̀ níwájú àwọn ọmọ ogun rẹ̀,nítorí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ,alágbára ni ẹni tí ń mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.Ọjọ́ ńlá ati ọjọ́ ẹ̀rù ni ọjọ́ OLUWA!Ta ló lè faradà á?

12. OLUWA ní, “Ẹ yipada sí mi tọkàntọkàn nisinsinyii,pẹlu ààwẹ̀, ẹkún ati ìkẹ́dùn,

13. Ìrònúpìwàdà tòótọ́ ni mò ń fẹ́,kì í ṣe pé kí ẹ fa aṣọ yín ya nìkan.”Ẹ yipada sí OLUWA Ọlọrun yín,nítorí olóore-ọ̀fẹ́ ati aláàánú ni.Kì í yára bínú,Ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀,a sì máa dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji eniyan.

14. Ó ṣeéṣe kí Ọlọrun ṣàánú, kí ó yí ibinu rẹ̀ pada,kí ó sì tú ibukun rẹ̀ sílẹ̀,kí ẹ lè rú ẹbọ ohun jíjẹ ati ẹbọ ohun mímu fún OLUWA Ọlọrun yín.

15. Ẹ fọn fèrè ní òkè Sioni,ẹ kéde ààwẹ̀ kí ẹ sì pe àpéjọ.

16. Ẹ pe gbogbo eniyan jọ,kí ẹ sì ya ìjọ eniyan sí mímọ́.Ẹ pe àwọn àgbààgbà jọ,ẹ kó àwọn ọmọde ati àwọn ọmọ ọwọ́ jọ.Kí ọkọ iyawo jáde láti inú yàrá rẹ̀,kí iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé náà jáde ninu yàrá rẹ̀.

17. Kí àwọn alufaa, àwọn iranṣẹ Ọlọrun, sọkún láàrin ẹnu ọ̀nà àbáwọlé ati pẹpẹ ìrúbọ.Kí wọ́n wí pé “OLUWA, dá àwọn eniyan rẹ sí,má sì sọ ilẹ̀ rẹ di ohun ẹ̀gàn ati ohun ẹ̀sín láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù.Má jẹ́ kí àwọn eniyan láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù bèèrè pé,‘Níbo ni Ọlọrun wọn wà?’ ”

18. Nígbà náà ni ara bẹ̀rẹ̀ sí ta OLUWA nítorí ilẹ̀ rẹ̀,ó sì ṣàánú fún àwọn eniyan rẹ̀.

Ka pipe ipin Joẹli 2