Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Joẹli 2:25-31 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Gbogbo ohun tí ẹ pàdánùní àwọn ọdún tí àwọn ọmọ ogun mi tí mo rán si yín ti jẹ oko yín;ati èyí tí eṣú wẹẹrẹ jẹ, ati èyí tí eṣú ńláńlá jẹ,gbogbo rẹ̀ ni n óo dá pada fun yín.

26. Ẹ óo jẹ oúnjẹ àjẹyó ati àjẹtẹ́rùn,ẹ óo sì yin orúkọ OLUWA Ọlọrun yín,tí ó ṣe ohun ìyanu ńlá fun yín,ojú kò sì ní ti àwọn eniyan mi mọ́ lae.

27. Ẹ óo mọ̀ pé mo wà láàrin Israẹli;ati pé èmi OLUWA ni Ọlọrun yín,kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi mọ́.Ojú kò sì ní ti àwọn eniyan mi mọ́ lae.

28. “Lẹ́yìn náà, nígbà tí ó bá yá,n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára gbogbo eniyan,àwọn ọmọkunrin ati àwọn ọmọbinrinyín yóo máa sọ àsọtẹ́lẹ̀,àwọn àgbààgbà yín yóo máa lá àlá,àwọn ọdọmọkunrin yín yóo sì máa ríran.

29. Bákan náà, nígbà tí àkókò bá tó,n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára àwọn iranṣẹkunrin ati àwọn iranṣẹbinrin yín.

30. “Ìtàjẹ̀sílẹ̀ yóo pọ̀,n óo sì fi iná, ati òpó èéfín sí ojú ọ̀run,ati sórí ilẹ̀ ayé;yóo jẹ́ ìkìlọ̀ fun yín.

31. Oòrùn yóo ṣókùnkùn,òṣùpá yóo pọ́n rẹ̀bẹ̀tẹ̀ bí ẹ̀jẹ̀,kí ọjọ́ OLUWA tí ó lẹ́rù tó dé.

Ka pipe ipin Joẹli 2