Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 9:7-25 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ó pàṣẹ fún oòrùn,oòrùn kò sì yọ;ó sé àwọn ìràwọ̀ mọ́lé;

8. òun nìkan ṣoṣo ni ó dá ojú ọ̀run tẹ́ bí aṣọ,tí ó sì tẹ ìgbì omi òkun mọ́lẹ̀.

9. Ó dá àwọn ìràwọ̀ sójú ọ̀run:Beari, Orioni, ati Pileiadesiati àwọn ìràwọ̀ ìhà gúsù.

10. Ó ṣe àwọn ohun ńlá tí ó kọjá òye ẹ̀dá,ati àwọn iṣẹ́ ìyanu tí kò ní òǹkà.

11. Ó gba ẹ̀gbẹ́ mi kọjá, n kò rí i,ó ń kọjá lọ, n kò sì mọ̀.

12. Wò ó! Ó já àwọn ohun tí ó wù ú gbà,ta ló lè dá a dúró?Ta ló tó bi í pé, ‘Kí ni ò ń ṣe?’

13. “Ọlọrun kò ní dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró,yóo fi ẹsẹ̀ tẹ àwọn olùrànlọ́wọ́ Rahabu mọ́lẹ̀.

14. Báwo ni mo ṣe lè bá a rojọ́?Kí ni kí n sọ?

15. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi,sibẹsibẹ n kò lè dá a lóhùn.Ẹ̀bẹ̀ nìkan ni mo lè bẹ̀ fún àánú,lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ẹ̀sùn kàn mí.

16. Bí mo bá pè é pé kó wá gbọ́,tí ó sì dá mi lóhùn,sibẹ n kò lè gbàgbọ́ pé yóo dẹtí sílẹ̀ gbọ́rọ̀ mi.

17. Nítorí pé ó ti fi ìjì tẹ̀ mí mọ́lẹ̀,ó sì sọ egbò mi di pupọ láìnídìí;

18. kò ní jẹ́ kí n mí,ìbànújẹ́ ni ó fi kún ọkàn mi.

19. Bí ó bá ṣe ti pé kí á dán agbára wò ni,agbára rẹ̀ pọ̀ tayọ!Bí ó bá sì jẹ́ pé ti ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́,ta ló lè pè é lẹ́jọ́?

20. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi,sibẹsibẹ ọ̀rọ̀ ẹnu mi yóo di ẹ̀bi rù mí;bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́ṣẹ̀,sibẹsibẹ yóo fihàn pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.

21. N kò lẹ́bi,sibẹ n kò ka ara mi kún,ayé sú mi.

22. Kò sí ìyàtọ̀ lójú rẹ̀,nítorí náà ni mo fi wí pé,ati ẹlẹ́bi ati aláìlẹ́bi ni ó ti parun.

23. Nígbà tí nǹkan burúkú bá ṣẹlẹ̀,tí ó já sí ikú òjijì,a máa fi aláìṣẹ̀ ṣe ẹlẹ́yà ninu ìdààmú wọn.

24. A ti fi ayé lé àwọn ẹni ibi lọ́wọ́,ó ti di àwọn adájọ́ rẹ̀ lójú.Bí kì í bá ṣe òun Ọlọrun,ta ló tún tó bẹ́ẹ̀?

25. “Ọjọ́ ayé mi ń sáré lọ tete,kò sí ẹyọ ọjọ́ kan tí ó dára ninu wọn.

Ka pipe ipin Jobu 9