Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 4:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:

2. “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀,ṣé kò ní bí ọ ninu?Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?

3. O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan,o ti fún aláìlera lókun.

4. O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró,ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.

5. Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́,o kò ní sùúrù;Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.

6. Ṣé ìbẹ̀rù Ọlọrun kò tó ìgboyà fún ọ?Àbí ìwà òdodo rẹ kò fún ọ ní ìrètí?

Ka pipe ipin Jobu 4